Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 31:24-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Ní ọjọ́ kéje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”

25. Olúwa sọ fún Mósè pé,

26. “Ìwọ àti Élíásárì àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbékùn.

27. Pín ohun ìní àti ìkógún náà láàrin àwọn ọmọ ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrin gbogbo ìjọ.

28. Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà: ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìnyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.

29. Gbà ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín ti wọn, kí o sì fún Élíásárì àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.

30. Lára ààbọ̀ ti Ísírẹ́lì, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, (50) yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Léfì, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”

31. Nígbà náà Mósè àti Élíásárì àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mósè.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 31