Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 26:60-65 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

60. Árónì ni baba Nádábù àti Ábíhù, Élíásárì àti Ítamárì.

61. Ṣùgbọ́n Nádábù àti Ábíhù kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)

62. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Léfì láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbàá mọ́kànlá ó lé lẹ́gbẹ̀rún (23,000). Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.

63. Àwọn wọ̀nyí ni Mósè àti Élíásárì àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Móábù lẹ́bá odò Jọ́dánì létí Jẹ́ríkò.

64. Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mósè àti Árónì àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ihà Sínáì.

65. Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kíkú ni wọn yóò kú sí ihà, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú à fi Kálẹ́bù ọmọ Jéfúnì, àti Jóṣúà ọmọ Núnì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 26