Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 26:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-àrùn Olúwa sọ fún Mósè àti Élíásárì ọmọ Árónì, àlùfáà pé

2. “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun (20) ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Ísírẹ́lì.”

3. Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Móábù pẹ̀lú Jọ́dánì tí ó kọjá Jẹ́ríkò, Mósè àti Élíásárì àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,

4. “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ ogun (20) ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mósè.”Èyí ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí ó jáde láti Éjíbítì wá:

5. Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àkọ́bí ọmọkùnrin Ísírẹ́lì,láti ẹni ti ìdílé Hánókù, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hánókù ti jáde wá;Láti ìdílé Pálù, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pálù ti jáde wá;

6. ti Hésírónì, ìdílé àwọn ọmọ Hésírónì;ti Kárímì, ìdílé àwọn ọmọ Kárímì.

7. Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Rúbẹ́nì; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé ẹgbẹ̀sán ó dín àádọ́rin (43,730).

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 26