8. “Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí” Bálámù sọ fún un pé, “Èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Móábù dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
9. Ọlọ́run tọ Bálámù wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
10. Bálámù sọ fún Ọlọ́run pé, “Bálákì ọmọ Sípórì, ọba Móábù, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé:
11. ‘Ènìyàn tí ó jáde láti Éjíbítì wá bo ojú ayé. Nísinsin yìí wá kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá màá le bá wọn jà èmi ó sì lé wọn jáde.’ ”
12. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Bálámù pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”