Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 21:21-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ísírẹ́lì rán oníṣẹ́ láti sọ fún Síhónì ọba àwọn ará Ámórì wí pé:

22. “Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀ èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà tàbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”

23. Ṣùgbọ́n Síhónì kò ní jẹ́ kí àwọn Ísírẹ́lì kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí ihà nítorí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Nígbà tí ó dé Jánásì, ó bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jà.

24. Àmọ́ Ísírẹ́lì ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Ánónì lọ dé Jábókù, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ámónì, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.

25. Ísírẹ́lì sì gba gbogbo ìlú Ámórì wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Hésíbónì, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.

26. Hésíbónì ni ìlú Ṣíhónì ọba àwọn ará Ámórì, ẹni tí ó bá ọba ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Ánónì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 21