Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 19:3-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ mú fún Élíásárì àlùfáà, yóò sì mu jáde lọ sí ẹ̀yìn ibùdó kí ó sì pa á ní ojú rẹ.

4. Nígbà náà ni Élíásárì àlùfáà yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sórí ìka ọwọ́ rẹ̀ yóò sì wọn lẹ́ẹ̀méje ní ọ̀kánkán iwájú àgọ́ ìpàdé.

5. Ní ojú rẹ̀ ni àlùfáà yóò ti sun ọ̀dọ́ abo màlúù yìí: awọ ara rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, ẹran ara àti ìgbẹ́ rẹ̀.

6. Àlùfáà yóò mú igi òpépé, hísópù àti òwú òdòdó yóò sì jù wọ́n sí àárin ọ̀dọ́ abo màlúù tí a ń sun.

7. Lẹ́yìn náà, Àlùfáà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, kí ó sì wẹ ara rẹ̀ pẹ̀lú omi lẹ̀yìn náà ó lè wá sínú àgọ́. Ṣùgbọ́n yóò jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́.

8. Ẹni tí ó sun ún náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀ kí ó sì wẹ̀ pèlú omi, òun náà yóò jẹ́ aláìmọ́ títi di ìrọ̀lẹ́.

9. “Ẹni tó wà ní mímọ́ ni yóò kó eérù ọ̀dọ́ màlúù náà lọ sí ibi tí a yà sí mímọ́ lẹ́yìn ibùdó. Kí gbogbo ìjọ ènìyàn Ísírẹ́lì kó o pamọ́ fún lílò fún omi ìwẹ̀nùmọ́. Ó jẹ́ ìwẹ̀nùmọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀.

10. Ọkùnrin tí ó kó eérú ọ̀dọ́ abo màlúù náà gbọdọ̀ fọ aṣọ rẹ̀, òun náà yóò sì jẹ́ aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà láéláé fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì àti fún àwọn àlejò tí ó ń gbé láàrin wọn.

11. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá fọwọ́kan òkú ẹnikẹ́ni, yóò jẹ́ aláìmọ́ fún ọjọ́ méje.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 19