Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 11:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Mósè sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà Ísírẹ́lì dúró yí àgọ́ ká.

25. Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ìkúùkù ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lárá Ẹ̀mí tó wà lára Mósè sí ara àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà náà, Ó sì sẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n ṣọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò ṣọtẹ́lẹ̀ mọ́.

26. Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Élídádì àti Médádì kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin (70) àgbààgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ ṣíbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì ṣọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.

27. Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mósè pé, “Élídádì àti Médádì ń ṣọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”

28. Jósúà ọmọ Núnì tí í ṣe ìránṣẹ́ Mósè, láti kékeré tó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dáhùn pé, “Mósè olúwa mi, dá wọn lẹ́kun!”

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 11