Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 11:19-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ẹ kò ní i jẹ ẹ́ fún ọjọ́ kan, ọjọ́ méjì, ọjọ́ márùn-ún, ọjọ́ mẹ́wàá tàbí ogúnjọ́ lásán,

20. Ṣùgbọ́n fún odidi oṣù kan: títí tí ẹran náà yóò fi máa yọ ní imú yín, tí yóò sì sú yín: nítorí pé ẹ ti kẹ́gàn Olúwa tí ó wà láàrin yín, ẹ sì ti sunkún fún un wí pé, “Kí ló dé tí a fi kúrò ní Éjíbítì gan-an?” ’ ”

21. Ṣùgbọ́n Mósè sọ pé, “Mo wà láàrin ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ènìyàn (600,000) ni ìrìnkirì, ó sì sọ pé, ‘Èmi ó fún wọn ní ẹran láti jẹ fún oṣù kan gbáko!’

22. Ǹjẹ́ bí a tilẹ̀ pa àgbò ẹran àti ọmọ ẹran, yóò ha tó wọn bí? Tàbí bí a tilẹ̀ pa gbogbo ẹja inú omi fún wọn, yóò wa tó bí?”

23. Olúwa sì dá Mósè lóhùn pé, “Ọwọ́ Olúwa ha kúrú bí? Ìwọ yóò ri nísinsin yìí bóyá ọ̀rọ̀ tí mo sọ yóò ṣẹ tàbí kò ni í ṣẹ.”

24. Mósè sì jáde, ó sọ ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn. Ó mú àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà Ísírẹ́lì dúró yí àgọ́ ká.

25. Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ìkúùkù ó sì bá wọn sọ̀rọ̀, ó sì mú lárá Ẹ̀mí tó wà lára Mósè sí ara àwọn àádọ́rin (70) àgbààgbà náà, Ó sì sẹlẹ̀ pé nígbà tí Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n ṣọtẹ́lẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí wọn kò ṣọtẹ́lẹ̀ mọ́.

26. Àwọn ọkùnrin méjì, tí orúkọ wọn ń jẹ́ Élídádì àti Médádì kò kúrò nínú àgọ́. Orúkọ wọn wà lára àádọ́rin (70) àgbààgbà yìí ṣùgbọ́n wọn kò jáde nínú àgọ́ ṣíbẹ̀ Ẹ̀mí náà bà lé wọn, wọ́n sì ṣọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.

27. Ọmọkùnrin kan sì sáré lọ sọ fún Mósè pé, “Élídádì àti Médádì ń ṣọtẹ́lẹ̀ nínú àgọ́.”

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 11