Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nọ́ḿbà 1:14-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Láti ọ̀dọ̀ Gáádì, Élíásàfu ọmọ Déúélì;

15. Láti ọ̀dọ̀ Náfítalì, Áhírà ọmọ Énánì.”

16. Àwọn wọ̀nyìí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Ísírẹ́lì.

17. Mósè àti Árónì mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí

18. wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Ísírẹ́lì jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì se àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,

19. gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paṣẹ fún Mósè. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú ihà Ṣínáì.

Ka pipe ipin Nọ́ḿbà 1