Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 9:2-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sì ya ara wọn ṣọ́tọ̀ kúrò nínú un gbogbo àwọn àlejò. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.

3. Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní ṣíṣin Olúwa Ọlọ́run wọn.

4. Nígbà náà ni Jéṣúà, àti Bánì, Kádímíélì, Ṣebaníà, Bunnì, Ṣeribíà, Bánì àti Kénánì gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Léfì, wọ́n si fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn

5. Nígbà náà ni àwọn ọmọ Léfì: Jéṣúà, Bánì, Háṣábínéáyà, Ṣérébáyà, Hódáyà, Ṣébánáyà àti Pétaíáyà—wí pé: “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.”“Ìbùkún ni fún orúkọ ọ̀ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.

Ka pipe ipin Nehemáyà 9