Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 6:15-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹ̀dọ́gbọ̀n oṣù Élúlì (oṣù kẹsán), láàrin ọjọ́ méjìléláàdọ́ta (52).

16. Nígbà tí àwọn ọ̀ta wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.

17. Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́láa Júdà ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tòbáyà, èsì láti ọ̀dọ̀ Tòbáyà sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.

18. Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júdà ti mulẹ̀ pẹ̀lú u rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekenáyà ọmọ Árà (Ṣáńbálátì fẹ́ ọmọ Ṣekenáyà) ọmọ rẹ̀ Jéhóhánánì sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Méṣúlámì ọmọ Bérékíyà

19. ṣíwájú sí í, wọ́n túnbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún-un. Tòbáyà sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rù bà mí.

Ka pipe ipin Nehemáyà 6