Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Nehemáyà 3:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Élíṣíbù olórí àlùfáà àti àwọn àlùfáà arákùnrin rẹ̀ lọ ṣiṣẹ́, wọ́n sì tún ibodè Àgùntàn mọ. Wọ́n yà á sí mímọ́, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn dúró sí ibi tí ó yẹ, wọ́n mọ ọ́n títí dé ilé ìṣọ́ Ọgọ́rùn ún, èyí tí wọ́n yà sí mímọ́ títí dé ilé ìṣọ́ gíga Hánálélì

2. Àwọn ọkùnrin Jẹ́ríkò sì mọ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Ṣákúrì ọmọ Ímírì sì mọ ní ẹ̀gbẹ̀ àwọn ọkùnrin Jẹ́ríkò.

3. Àwọn ọmọ Háṣénáyà ni wọ́n mọ Ìbodè Ẹja. Wọ́n kún bíìmù rẹ̀, wọ́n sì gbé ìlẹ̀kùn rẹ̀, ìdábùú ìlẹ̀kùn àti àwọn ìdè e rẹ̀ sí ààyè e wọn.

4. Mérémótì ọmọ Úráyà, ọmọ Hákóṣì tún èyí tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ẹ wọn mọ. Ẹni tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni Mésúlámù ọmọ Bérékíà, ọmọ Méṣéábélì tún èyí ti ó wà ní ẹ̀gbẹ́ẹ wọn mọ. Bákan ńaà ni ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, Ṣádókù ọmọ Báánà náà tún odi mọ.

5. Èyí tí ó tún wà ní ẹ̀gbẹ́ wọn ni àwọn ọkùnrin Tẹ́kóà tún mọ, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́lá kò ṣe àtìlẹ́yìn fún iṣẹ́ náà lábẹ́ àwọn olórí wọn.

Ka pipe ipin Nehemáyà 3