Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Náhúmù 3:17-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,èyí ti ń dó sínú ọgbà la ọjọ́ òtútù,ṣùgbọ́n nígbà tí òòrùn jáde, wọ́n sá lọẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

18. Ìwọ ọba Ásíríà,àwọn olùṣọ àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;awọn ọlọ́lá rẹ yóò máa gbé inú ekuru.Rẹ àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,tí ẹnikẹni kò sì kó wọn jọ.

19. Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ rẹ sàn;ọgbẹ́ rẹ kun fún ìroraGbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹyóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,nítorí ni orí ta ni,ìwà buburu rẹ kò ti kọjá nígbà gbogbo?

Ka pipe ipin Náhúmù 3