Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Míkà 1:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Míkà ará Mórésétì wá ní àkókò ìjọba Játamù, Áhásì, àti Heṣekáyà, àwọn ọba Júdà nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaríà àti Jérúsálẹ́mù.

2. Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn,fétísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀,kí Olúwa alààyè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹ́ḿpìlì mímọ́ rẹ̀ wá.

3. Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀;yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.

4. Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀,àwọn àfonífojì yóò sì pín yà,bí idà níwájú iná,bí omi tí ó ń ṣàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.

Ka pipe ipin Míkà 1