Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 27:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa sọ fún Móse pé.

2. “Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé: ‘Bí ẹnìkan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì láti ya ènìyàn kan sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run nípa sísan iye tí ó tó,

3. kí iye owó ọkùnrin láti ọmọ ogún ọdún sí ọgọ́ta ọdún jẹ́ àádọ́ta òṣùnwọ̀n Ṣékélì fàdákà, gẹ́gẹ́ bí oṣùwọ̀n sékélì ti ibi mímọ́ Olúwa;

4. Bí ẹni náà bá jẹ obìnrin, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ ọgbọ̀n òṣùwọ̀n sékéli.

5. Bí ẹni náà bá jẹ́ ọmọ ọdún márùn-ún sí ogún ọdún, kí iye owó rẹ̀ jẹ́ ogún ṣékélì fún ọkùnrin àti òṣùwọ̀n ṣékélì mẹ́wàá fún obìnrin.

Ka pipe ipin Léfítíkù 27