53. Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
54. “ ‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
55. Torí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Éjíbítì wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.