Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 24:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Sọ fún àwọn ará Ísírẹ́lì pé: ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

16. Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọbíbí Ísírẹ́lì, bí ó bá ti sọ̀rọ̀òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.

17. “ ‘Ẹni tí ó bá gba ẹmi ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.

18. Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.

19. Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára: ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.

20. Bí ó bá ṣẹ́ egungun ẹnìkan, egungun tirẹ̀ náà ni kí a ṣẹ́, bí ó bá fọ́ ojú ẹnìkan, ojú tirẹ̀ náà ni kí a fọ́, bí ó bá ká eyín ẹnìkan, eyín tirẹ̀ náà ni kí a ká. Bí ó ti pa ẹnìkejì lára náà ni kí ẹ pa òun náà lára.

Ka pipe ipin Léfítíkù 24