Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 13:56-59 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

56. Bí àlùfáà bá yẹ̀ ẹ́ wò ti ẹ̀tẹ̀ náà bá ti kúrò níbẹ̀: lẹ́yìn tí a ti fọ̀ ohunkóhun tí ó mú, kí ó ya ibi tí ó bàjẹ́ kúrò lára aṣọ náà, awọ náà, aṣọ híhun náà tàbí aṣọ tìta náà.

57. Ṣùgbọ́n bí ó bá tún ń farahàn níbi aṣọ náà, lára aṣọ títa náà, lára aṣọ híhun náà tàbí lára ohun èlò awọ náà, èyí fi hàn pé ó ń ràn ká. Gbogbo ohun tí ẹ̀tẹ̀ náà bá wà lára rẹ̀ ni kí ẹ fí iná sun.

58. Aṣọ náà, aṣọ títa náà, aṣọ híhun náà tàbí ohun èlò àwọ náà tí a ti fọ̀ tí ó sì mọ́ lọ́wọ́ ẹ̀tẹ̀ náà ni kí a tún fọ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i. Yóò sì di mímọ́.”

59. Ìlànà wọ̀nyí wà fún àwọn ohun tí ẹ̀tẹ̀ bàjẹ́ níbi, aṣọ irun àgùtàn aṣọ funfun, aṣọ títa, aṣọ híhun tàbí ohun èlò awọ, láti fi hàn bóyá wọ́n wà ní mímọ́ tàbí àìmọ́.

Ka pipe ipin Léfítíkù 13