Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 11:4-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. “ ‘Àwọn mìíràn wà tó ń jẹ àpọ̀jẹ nìkan. Àwọn mìíràn wà tó jẹ́ pé pátakò ẹsẹ̀ wọn nìkan ni ó là, ìwọ̀nyí ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ fún àpẹrẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ràkunmí ń jẹ àpọ̀jẹ kò ya pátakò ẹsẹ̀, àìmọ́ ni èyí jẹ́.

5. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé gára (ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta) ń jẹ apojẹ àìmọ́ lèyí jẹ́ fún yín.

6. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ehoro ń jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n kò ya pátakò ẹsẹ̀: àìmọ́ lèyí jẹ́ fún yín.

7. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹlẹdẹ́ ya pátakò ẹṣẹ̀ ṣùgbọ́n kì í jẹ àpọ̀jẹ àìmọ́ lèyí jẹ́ fún yín.

8. Ẹ má ṣe jẹ ẹran wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú wọn. Àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.

9. “ ‘Nínú gbogbo ohun tí Ọlọ́run dá tí ń gbé inú omi òkun, àti nínú odò: èyíkéyí tí ó bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́ ni ẹ lè jẹ́.

10. Ṣùgbọ́n nínú gbogbo ẹ̀dá tí ń gbé inú òkun àti nínú odò tí kò ní lẹbẹ àti ìpẹ́, yálà nínú gbogbo àwọn tí ń rákò tàbí láàrin gbogbo àwọn ẹ̀dá alààyè yòókù tí ń gbé inú omi àwọn ni kí ẹ kórìíra.

11. Nígbà tí ẹ ti kórìíra wọn ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran wọn: ẹ gbọdọ̀ kórìíra òkú wọn.

12. Ohunkóhun tí ń gbé inú omi tí kò ní lẹbẹ àti ìpẹ́ gbọdọ̀ já sí ìríra fún yín.

13. “ ‘Àwọn ẹyẹ wọ̀nyí ni ẹ gbọdọ̀ kórìíra tí ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ wọ́n torí pé ohun ìríra ni wọ́n: idì, oríṣìiríṣìi igun,

14. Àwòdì àti onírúurú àṣá,

15. Onírúurú ẹyẹ ìwò,

16. Òwìwí, onírúurú ògòǹgò, onírúurú ẹ̀lúùlú, onírúurú àwòdì,

17. Òwìwí kéékèèkéé, onírúurú òwìwí,

Ka pipe ipin Léfítíkù 11