Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Léfítíkù 1:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa sì pe Mósè, ó sì bá a sọ̀rọ̀ láti inú àgọ́ àjọ. Ó wí pé;

2. “Bá àwọn ọmọ Ísírẹ́lì sọ̀rọ̀ kí o sì wí fún wọn pé: ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín bá mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, kí ọrẹ ẹbọ yín jẹ́ ẹran ọ̀sìn láti inú agbo ẹran tàbí láti inú ọ̀wọ́ ẹran.

3. “ ‘Bí ọrẹ ẹbọ náà bá jẹ́ sísun láti inú agbo ẹran kí òun kí ó mú akọ màlúù tí kò lábùkù. Ó sì gbọdọ̀ múu wá sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ kí ó bá à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà níwájú Olúwa

4. kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé orí ẹbọ sísun náà yóò sì jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà dípò o rẹ̀, yóò sì jẹ́ ètùtù fún un.

5. Kí ó pa ọ̀dọ́ akọ màlúù náà níwájù Olúwa, lẹ́yìn náà ni àwọn àlùfáà tí í se ọmọ Árónì yóò gbé ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ náà yí pẹpẹ tí ó wà ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ ká.

6. Òun yóò bó àwọ ara akọ ọ̀dọ́ màlúù náà, òun yóò sì gé e sí wẹ́wẹ́.

Ka pipe ipin Léfítíkù 1