Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 7:19-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Nígbà náà ní Jóṣúà sọ fún Ákánì pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì, kí o sì fi ìyin fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”

20. Ákánì sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì. Nǹkan tí mo ṣe nì yí:

21. Nígbà tí mo rí ẹ̀wù Bábílónì kan tí ó dára nínú ìkógún, àti igba sẹ́kélì fàdákà àti díndi wúrà olóṣùnwọ̀n àádọ́ta ṣẹ́kélì, mo ṣe ojú kòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ ọ̀ mi àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.”

22. Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì ṣáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.

23. Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Jóṣúà àti gbogbo àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.

24. Nígbà náà ni Jóṣúà pẹ̀lú gbogbo Ísírẹ́lì, mú Ákánì ọmọ Sérà, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Ákórì.

Ka pipe ipin Jóṣúà 7