Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 21:33-45 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gáṣónì jẹ́ mẹ́talá, pẹ̀lú ilẹ́ pápá oko wọn.

34. Láti ara ẹ̀yà Sébúlónì ni a ti fún ìdílé Mérárì (tí í ṣe ìyókù ọmọ Léfì) ní:“Jókíníámù, Kárítà,

35. Dímínà àti Náhálálì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.

36. Láti ara ẹ̀yà Rúbẹ́nì ni wọ́n ti fún wọn níBésérì, àti Jáhásì,

37. Kédémótì àti Mẹ́fátì, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ mẹ́rin.

38. Láti ara ẹ̀yà Gádì ní wọ́n ti fún wọn níRámótìa ní Gílíádì (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Máhánáímù,

39. Hésíbónì àti Jásérì, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.”

40. Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Mérárì tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Léfì jẹ́ méjìlá.

41. Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Léfì tó wà láàárin ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jẹ́ méjìdínláádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.

42. Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.

43. Báyìí ni Olúwa fún Ísírẹ́lì ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi àwọn fún baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.

44. Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti sèlèrí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀ta wọn tí ó lè dojú kọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀ta wọn lé wọn ní ọwọ́.

45. Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí ó se fún ilé Ísírẹ́lì tí ó kùnà. Gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.

Ka pipe ipin Jóṣúà 21