Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 2:10-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì; àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Ṣíhónì àti Ógù, àwọn ọba méjèèjì ti Ámórì ti ìlà-oòrùn Jọ́dánì, tí ẹ̀yin parun pátapáta.

11. Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí; ọkàn an wa pámi, kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.

12. Ǹjẹ́ nísinsìnyìí, ẹ jọ̀wọ́, ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ fún mi ní àmì tó dájú:

13. pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábinrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”

14. “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”

15. Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.

16. Ó sì ti ṣọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má baà rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”

17. Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa baà lè mọ́ kúró nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.

18. Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò ṣo okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.

19. Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú ù rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní órí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.

20. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwá ń se, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”

21. Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀.” “Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí ṣọ.” Ó sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú u-fèrèsé.

Ka pipe ipin Jóṣúà 2