Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 2:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni Jóṣúà ọmọ Núnì rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àsírí láti Ṣítímù. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jẹ́ríkò.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé aṣẹ́wó kan, tí à ń pè ní Ráhábù, wọ́n sì dúró síbẹ̀.

2. A sì sọ fún ọba Jẹ́ríkò, “Wò ó! Àwọn ará Ísírẹ́lì kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”

3. Ọba Jẹ́ríkò sì ránṣẹ́ sí Ráhábù pé: “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”

4. Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà, o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “lóótọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.

5. Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò làti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”

6. (Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà, ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)

7. Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn amí náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jọ́dánì, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.

8. Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.

9. Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí, àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí iyín.

10. Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì; àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Ṣíhónì àti Ógù, àwọn ọba méjèèjì ti Ámórì ti ìlà-oòrùn Jọ́dánì, tí ẹ̀yin parun pátapáta.

11. Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí; ọkàn an wa pámi, kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.

12. Ǹjẹ́ nísinsìnyìí, ẹ jọ̀wọ́, ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ fún mi ní àmì tó dájú:

13. pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábinrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”

14. “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”

Ka pipe ipin Jóṣúà 2