Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 19:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Bẹti-Lébà ati Ṣárúẹ́nì, ìlú wọn jẹ́ mẹ́talá àti ìletò wọn.

7. Háínì, Rímónì, Étérì àti Áṣánì: Ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn:

8. Àti gbogbo àwọn agbégbé ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Béérì (Rámà ní Négéfì).Èyí ni ìní àwọn ọmọ Símíónì, agbo ilé, ní agbo ilé.

9. A mú ogún ìní àwọn ọmọ Símíónì láti ìpín Júdà, nítorí ìpín Júdà pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Símíónì gba ìní wọn ní àárin ilẹ̀ Júdà.

10. Gègé kẹ́ta jáde fún Sébúlunì, ní agbo ilé ní agbo ilé:Ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Sárídì.

11. Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Márálà, ó sì dé Dábésẹ́tì, ó sì lọ títí dé Ráfénì odo ní ẹ̀bá Jókíníámù.

12. Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Sérídì sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tábórì, ó sì lọ sí Dábérátì, ó sì gòkè lọ sí Jáfíà.

13. Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Héférì àti Eti-Kásínì, ó sì jáde ní Rímónì, ó sì yí sí ìhà Níà.

14. Ní ibẹ̀, ààlà sì yí ká ní ìhà àríwá lọ sí Hánátónì ó sì pin ní Àfonífojì Ifita Élì.

15. Lára wọn ni Kátatì, Náhalálì, Símírónì, Ìdálà àti Bẹ́tílẹ́hẹ́mù. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.

16. Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sébúlunì, ní agbo ilé agbo ilé.

17. Gègé kẹrin jáde fún Ísákárì, agbo ilé ní agbo ilé.

Ka pipe ipin Jóṣúà 19