Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 19:32-46 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Ìpín kẹfà jáde fún Náfítalì, agbo ilé ní agbo ilé:

33. Ààlà wọn lọ láti Hẹ́lẹ́fì àti igi ńlá ní Sááná nímù; kọjá lọ sí Ádámì Nékébù àti Jábínẹ́ẹ́lì dé Lákúmì, ó sì pín ní Jọ́dánì.

34. Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Ásínótì, Tabori ó sì jáde ní Húkókì. Ó sì dé Sébúlúnìe ní ìhà gúsù, Ásíẹ́rì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Jọ́dánì ní ìhà ìlà-oòrùn.

35. Àwọn ìlú olódi sì Sídímù, Sérì, Hámátì, Rákátì, Kínérétì,

36. Ádámà, Rámà Hásórì,

37. Kédéṣì, Édíréì, Ẹ́ní-Hásórì,

38. Írónì, Mígídálì-Élì, Hórémù, Bẹ́tì-Ánátì àti Bẹ́tì-Sẹ́mẹ́ṣì. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.

39. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Náfitalì, ní agbo ilé sí agbo ilé.

40. Ìbò keje jáde fún ẹ̀yà Dánì, ní agbo ilé ní agbo ilé.

41. Ilẹ̀ ìní wọn nì wọ̀nyí:Sórà, Éṣtaólì, Írí-Ṣẹ́mẹ́sì,

42. Ṣáálábínì, Áíjálónì, Ítílà,

43. Élónì, Tímínà, Ékírónì,

44. Élítékè, Gíbétónì, Báálátì,

45. Jéúdì, Béné-Bérákì, Gátí-Rímónì,

46. Mé Jákónì àti Rákónì, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Jópà.

Ka pipe ipin Jóṣúà 19