Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 19:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gègé kéjì jáde fún ẹ̀yà Símíónì, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárin ilẹ̀ Júdà.

2. Lára ìpín wọn ní:Béérí Ṣébà (tàbí Ṣẹ́bà), Móládà,

3. Hasari-Ṣúálì, Báláhì, Ésémù,

4. Élítóládì, Bétúlì, Hómà,

5. síkílágì, Bẹti-Mákábótì, Hasari-Súsà,

6. Bẹti-Lébà ati Ṣárúẹ́nì, ìlú wọn jẹ́ mẹ́talá àti ìletò wọn.

7. Háínì, Rímónì, Étérì àti Áṣánì: Ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn:

8. Àti gbogbo àwọn agbégbé ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Béérì (Rámà ní Négéfì).Èyí ni ìní àwọn ọmọ Símíónì, agbo ilé, ní agbo ilé.

9. A mú ogún ìní àwọn ọmọ Símíónì láti ìpín Júdà, nítorí ìpín Júdà pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Símíónì gba ìní wọn ní àárin ilẹ̀ Júdà.

10. Gègé kẹ́ta jáde fún Sébúlunì, ní agbo ilé ní agbo ilé:Ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Sárídì.

11. Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Márálà, ó sì dé Dábésẹ́tì, ó sì lọ títí dé Ráfénì odo ní ẹ̀bá Jókíníámù.

Ka pipe ipin Jóṣúà 19