Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 18:9-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Jóṣúà lọ ní ibùdó ní Ṣílò.

10. Jóṣúà sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Sílò ní iwájú Olúwa, Jóṣúà sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Ísírẹ́lì gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.

11. Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàárin ti ẹ̀yà Júdà àti Jósẹ́fù:

12. Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jọ́dánì, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jẹ́ríkò ní ìhà àríwá, ó sì forílé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí asálẹ̀ Bẹti-Áfẹ́nì.

13. Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúsù ní ọ̀nà Lúsì, (èyí ni Bẹ́tẹ́lì) ó sìdé Afaroti-Ádárì, ní orí òkè tí ó wà ní gúsù Bẹti-Hórónì

14. Láti òkè tí ó kọjú sí Bẹti-Hórónì ní gúsù ààlà náà yà sí gúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Báálì (tí í ṣe Kiriati-Jéárímù), ìlú àwọn ènìyàn Júdà. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.

15. Ìhà gúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jéárímù ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nẹ́fítóà.

16. Ààlà náà lọ sí ìṣàlẹ̀ ẹṣẹ̀ òkè tí ó kọjú sí Àfonífojì Bẹni-Hínómù, àríwá Àfonífojì Réfáímù O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Àfonífojì Hínómù sí apá gúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jébúsì, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé Ẹbi Rósẹ́lì.

17. Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni Ṣẹ́mẹ́sì, ó tẹ̀ṣíwájú dé Gélíótì tí ó kọjú sí òkè Pasi Ádúmímù, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Okúta Bóhánì ọmọ Rúbẹ́nì.

18. Ó tẹ̀ṣíwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Bẹti-Árábà, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.

19. Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Bẹti-Hógíládì, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jọ́dánì ní gúsù. Èyí ni ààlà ti gúsù.

20. Odò Jọ́dánì sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn.Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó ṣàmì sí ìní àwọn ìdílé Bẹ́ńjámínì ní gbogbo àwọn àyíká wọn.

21. Ẹyà Bẹ́ńjámínì ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí:Jẹ́ríkò, Bẹti-Hógílà, Emeki-Késísì,

Ka pipe ipin Jóṣúà 18