Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 17:15-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Jóṣúà dá wọn lóhùn pé, “Bí ẹ bá pọ̀ bẹ́ẹ̀, tí òkè ìlú Éfúráímù bá kéré fún yin, ẹ gòkè lọ sí igbó kí ẹ sì sán ilẹ̀ òkè fún ara yín ní ibẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn ará Pérísì àti ará Réfì.”

16. Àwọn ènìyàn Jósẹ́fù dáhùn, “Òkè kò tó fún wa, bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ará Kénánì tí ó gbé ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti gbogbo àwọn tí ń bẹ ní Bẹti-Ṣánì àti àwọn ìletò àti àwọn tí ń gbé ní àfonífojì Jésírẹ́ẹ́lì ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin.”

17. Ṣùgbọ́n Jóṣúà sọ fún àwọn ilé Jósẹ́fù: fún Éfúráímù àti Mánásè pé, “Lóòtọ́ ni ẹ pọ̀ lọ́pọ̀lọpọ̀, ẹ sì jẹ́ alágbára. Ẹ̀yin kí yóò sì ní ìpín kan ṣoṣo.

Ka pipe ipin Jóṣúà 17