Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóṣúà 15:17-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ótíniẹ́lì ọmọ Kénásì, arákùnrin Kélẹ́bù, sì gbà á, báyìí ni Kélẹ́bù sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Ákísà fún un ní ìyàwó.

18. Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Ákísà lọ sí ọ̀dọ̀ Ótíniẹ̀lì, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà nàà ni Ákísà sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kélẹ́bù sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”

19. Ó sì dáhùn pé, “Ṣe ojúrere àtàtà fún mi. Níwọ̀n ìgbà tí o ti fún mi ní ilẹ̀ ní Negefi fun mi ní ìsun omi pẹ̀lú.” Báyìí ni Kélẹ́bù fún un ní ìsun omi ti òkè àti ti ìṣàlẹ̀.

20. Èyí ni ilẹ̀ ini ẹ̀yà àwọn ọmọ Júdà gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.

21. Ìlú ìpẹ̀kun gúsù ti ẹ̀yà Júdà ní Négéfi ní ààlà Édómù niwọ̀nyí:Kabísélì, Édérì, Jágúrì,

22. Kínà, Dímónà, Ádádà,

23. Kédéṣì, Hásórì, Ítina,

24. Sífì, Télémù, Bíálótì,

Ka pipe ipin Jóṣúà 15