Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 7:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Sé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀?Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?

2. Bí ọmọ-ọ̀dọ̀ tí máa ń kanjú bojúwo òjíjìàti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.

3. Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù,òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.

4. Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, ‘Èmi wí pé nígbà wo ni èmi ó dìde?’Tí òru yóò sì kọjá? Ó sì tó fún mi láti yí síhìn-ín yí sọ́hùn-únTítí yóò fi di ògúlùtu erùpẹ̀ ti a fi wọ̀ mí ní aṣọ,àwọ̀ mi bù, ó sì di sísun ni.

5. Kòkòrò àti ògúlùtu erúpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ,awọ ara mi bù, o sì di sísun.

6. “Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ,o sì di lílò ní àìní ìrètí.

Ka pipe ipin Jóòbù 7