Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 4:2-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?

3. Kíyèsí i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.

4. Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.

5. Ṣùgbọ́n nísinsìnyí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọ lù ọ́;ara rẹ kò lélẹ̀.

6. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹàti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

7. “Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?

8. Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń se ìtùlẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.

9. Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.

10. Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnníunàti eyín àwọn ẹ̀gbọ̀rọ̀ kìnnìún ní a ká.

11. Ógbó kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,àwọn ẹ̀gbọrọ kìnnún sísanra ni a túká kiri.

12. “Ǹjẹ́ nísinsìn yìí a fí ohun lílùmọ́ kan hàn fún mi,etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.

13. Ní ìrò ínú lojú ìrán òru,nígbà tí oorun èjìkà kùn ènìyàn.

14. Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrìtí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.

15. Nígbà náà ni iwin kan kọjá lọ ní iwájú mi,irun ara mi dìde ró ṣánṣán.

16. Ó dúró jẹ́ẹ́,ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,àwòrán kan hàn níwájú mi,ìdákẹ́ rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:

Ka pipe ipin Jóòbù 4