12. “Ǹjẹ́ nísinsìn yìí a fí ohun lílùmọ́ kan hàn fún mi,etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13. Ní ìrò ínú lojú ìrán òru,nígbà tí oorun èjìkà kùn ènìyàn.
14. Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrìtí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15. Nígbà náà ni iwin kan kọjá lọ ní iwájú mi,irun ara mi dìde ró ṣánṣán.
16. Ó dúró jẹ́ẹ́,ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,àwòrán kan hàn níwájú mi,ìdákẹ́ rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:
17. ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo níwájú Ọlọ́run,ènìyàn kò ha le mọ̀ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18. Kíyèsí i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,nínú àwọn ańgẹ́lì rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀
19. Áńbọ̀ńtórí àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,ẹni tí ìbílẹ̀ wọ́n jẹ́ sí erùpẹ̀tí yóò di rírun kòkòrò.
20. A pa wọ́n run láti òwúrọ̀di alẹ́, wọ́n gbé láé láìrí ẹni kà á sí.