7. Òun kì ímú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo,ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́nwà lórí ìtẹ́; Àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
8. Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí asì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
9. Nígbà náà ni o ń sọ àwọn ohun tíwọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ́lú ìgbéraga wọn.
10. Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ósì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedéédéé.
11. Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín,wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀ra, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
12. Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́,wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
13. “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní àyékó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá dà wọ́n.
14. Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú níèwe, ẹ̀mí wọn a sì wà nínú àwọn oníwà Sódómù.
15. Òun gba òtòsì nínú ìpọ́njú wọn,a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínu ìnira wọn.
16. “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó sì dè ọ lọ látiinú ìhágágá síbi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálànínú rẹ̀ ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ a jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
17. Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọnbúburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
18. Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹmáa bàà tàn ọ́; láti jẹ́ kí títóbi èyà mú ọ sìnà.
19. Ọ̀rọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fidé bá ọ bí? Tàbi ipa agbára rẹ?
20. Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń kéàwọn orilẹ̀ èdè kúrò ní ipò wọn.
21. Máa sọra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀padà sí búrubú; Nítori èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
22. “Kíyèsí i, Ọlọ́run á gbé-ni-ga nípaagbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí òun?