Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 34:6-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò níàwòtán dídì ọgbẹ́.’

7. Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jóòbù,tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?

8. Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ósì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.

9. Nítorí ó sá ti wí pé,‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,tí yóò fí máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10. “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetí sílẹ̀ sí miẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:Ódodi fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú àti fúnOlódùmárè, tí yóò fí ṣe àìṣedéédéé!

11. Nítorí pé ó ń sá fún ènìyàn fúnohun tí a bá ṣe, yóò sì múolúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.

12. Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkúwà;bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.

13. Ta ni ó yàn ań lórí, tàbí ta ni ófi gbogbo ayé lée lọ́wọ́?

14. Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,

15. gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16. “Ǹjẹ́ nisinsìnyí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí;fetísí ohùn ẹnu mi.

17. Ẹni tí ó kóríra òtítọ́ ha le iṣe olóríbí? Ìwọ ó hà sì dá olóótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?

18. O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ènìyàn búburú ní ìwọ,tàbí fún àwọn ọmọ aládé pé, ìkà ni ẹ̀yin;

19. Ańbọ̀tórí fún ẹni tí kì í ṣójúṣàájú àwọn ọmọ-aládétàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí talákà lọ.Nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?

20. Ní ìṣẹ́jú kán ni wọn ó kú, láàrin ọ̀gànjọ́àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́, wọn a sì kọjá lọ;A sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21. “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa-ọ̀nàènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22. Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí ojìjìikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.

23. Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsíẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọsínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24. Òun ó sì fọ́ àwọn alágbáratúútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmìíràn dípò wọn,

Ka pipe ipin Jóòbù 34