Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 34:21-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa-ọ̀nàènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.

22. Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí ojìjìikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.

23. Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsíẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọsínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.

24. Òun ó sì fọ́ àwọn alágbáratúútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmìíràn dípò wọn,

25. nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yíwọn po ní òru; bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ́rẹ́ pọ̀.

26. Ó kọlù wọ́n nítorí ìwàbúburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmìíràn rí i,

27. nítorí pé wọ́n padà sẹ́yìndà sí i,wọn kò sì fi yè sí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,

28. kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkúnàwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òunsì gbọ́ igbe ẹkún aláìní

29. ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bápa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe é orilẹ̀ èdè tàbi sí ènìyàn kan ṣoṣo;

30. Kí àgàbàgebè kí ó má báà jọbakí wọn kí ó má di ìdẹ̀wò fún ènìyàn.

31. “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fúnỌlọ́run pé, èmi jẹ̀bí; èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?

32. Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bimo bá sì dẹ́sẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.

33. Íṣe bí ti inú rẹ̀ pe òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bíìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́ tàbíìwọ ìbá fẹ́ kì í ṣe èmi; Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ!

34. “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fúnmi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,

35. ‘Jóòbù ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣealáìgbọ́n.’

36. Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jóòbù wò déòpin, nítorí ìdahùn rẹ̀ dà bí i ti ènìyàn búburú:

37. Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ópàtẹ́wọ́ ní àárin wa, ó sì sọọ̀rọ̀ di púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

Ka pipe ipin Jóòbù 34