Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 28:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àtiibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.

2. Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin,bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.

3. Ènìyàn ni ó parí òkùnkùn, ó sì ṣeàwárí òkúta òkùnkùn àti tiinú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.

4. Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jìn sí àwọn tíń gbé òkè, àwọn tí ẹṣẹ̀ ènìyàngbàgbé; wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.

5. Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá,àti ohun tí ó wà ní ìṣàlẹ̀ ni ó yí sókè bí ẹni pé iná.

6. Òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta Sáfírì, o sìní erùpẹ̀ wúrà.

7. Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojúgúnnugún kò rí i rí;

8. Àwọn ẹrankan agbéraga kò rìn ibẹ̀rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.

Ka pipe ipin Jóòbù 28