Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 27:6-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Òdodo mi ni èmi dìmú ṣinṣin,èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyàmi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.

7. “Kí ọ̀ta mi kí ó dàbí ènìyànbúburú, àti ẹni tí ń dìde sími kí ó dàbí ẹni aláìsòdodo.

8. Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?

9. Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,nígbà tí ìpọ́jú bá dé sí i?

10. Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?Òun ha lé máa képe Ọlọ́run nígbà gbogbo?

11. “Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run:ọ̀nà tí ńbẹ lọ́dọ̀Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.

12. Kíyèsí i, gbogbo yín ni ó ti rí i;nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe já sí asán pọ̀ bẹ́ẹ̀?

13. “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọnaninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmáre:

14. Bí àwọn ọmọ rẹ bá di púpọ̀, fúnidà ni; àwọn ọmọ ọmọ rẹ̀ kì yóò yó fún oúnjẹ.

15. Àwọn tí ó kú nínú tirẹ̀ ni a ósìnkú nínú àjàkálẹ̀-àrùn: àwọnopó rẹ̀ kì yóò sì sunkún fún wọn.

16. Bí ó tilẹ̀ kó fàdákà jọ bí erùpẹ̀, tíó sì dá aṣọ jọ bí amọ̀;

17. Àwọn ohun tí ó tò jọ àwọnolóòótọ́ ni yóò lò ó; àwọnaláìṣẹ̀ ni yóò sì pín fàdákà rẹ̀.

Ka pipe ipin Jóòbù 27