Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 27:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Pẹ̀lúpẹ̀lú Jóòbù sì tún sọ kún ọ̀rọ̀ òwe rẹ̀, ó sì wí pé:

2. “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, ẹni tí ógba ìdájọ́ mi lọ, àti Olódùmárè tí ó bà mi ní ọkàn jẹ́;

3. (Níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀mí mi ń bẹ nínúmi, àti tí ẹ̀mi Ọlọ́run ń bẹ nínú ihò imú mi.)

4. Ètè mi kì yóò sọ̀rọ̀ èké, Bẹ́ẹ̀ niahọ́n mi kì yóò sọ̀rọ̀ ẹ̀tàn.

5. Kí a má ríi pé èmi ń dá yín láre;títí èmi ó fi kú, èmi kì yóò sí ìwà òtítọ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi.

6. Òdodo mi ni èmi dìmú ṣinṣin,èmi kì yóò sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́; àyàmi kì yóò sì gan ọjọ́ kan nínú ọjọ́ ayé mi.

7. “Kí ọ̀ta mi kí ó dàbí ènìyànbúburú, àti ẹni tí ń dìde sími kí ó dàbí ẹni aláìsòdodo.

8. Nítorí kí ni ìrètí àgàbàgebè,nígbà tí Ọlọ́run bá ké ẹ̀mí rẹ̀ kúrò, nígbà tí ó sì fà á jáde?

9. Ọlọ́run yóò ha gbọ́ àdúrà rẹ̀,nígbà tí ìpọ́jú bá dé sí i?

10. Òun ha le ní inú dídùn sí Olódùmarè?Òun ha lé máa képe Ọlọ́run nígbà gbogbo?

11. “Èmi ó kọ́ yín ní ẹ̀kọ́ ní ti ọwọ́ Ọlọ́run:ọ̀nà tí ńbẹ lọ́dọ̀Olódùmarè ni èmi kì yóò fi pamọ́.

12. Kíyèsí i, gbogbo yín ni ó ti rí i;nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe já sí asán pọ̀ bẹ́ẹ̀?

13. “Ẹ̀yin ni ìpín ènìyàn búburú lọ́dọ̀ Ọlọ́run, àti ogún àwọnaninilára, tí wọ́n ó gbà lọ́wọ́ Olódùmáre:

Ka pipe ipin Jóòbù 27