Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 26:5-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. “Àwọn aláìlágbára ti iṣà òkúwárìrì, lábẹ́ omi pẹ̀lú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

6. Ìhòòhò ni ipò òkú níwájú Ọlọ́run,ibi ìparun kò sí ní ibojì.

7. Òun ní o nà ìhà àríwá ọ̀run ní ibiòfùrufú, ó sì fi ayé rọ̀ ní ojú òfo.

8. Ó di omi pọ̀ nínú ìkùùkù àwọsánmọ̀rẹ̀ tí ó nípọn; àwọsánmọ̀ kò sì ya nísàlẹ̀ wọn.

9. Ó sì fa ojú ìtẹ́ rẹ̀ sẹ́yìn, ó sì tẹàwọsánmọ̀ rẹ̀ sí i lórí.

10. Ó fi idẹ yí omi òkun ká, títí déààlà ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn.

11. Ọ̀wọ̀n òpó ọ̀run wárìrì, ẹnu sì yàwọ́n sì ìbàwí rẹ̀.

12. Ó fi ipá rẹ̀ dààmú omi òkun; nípaòye rẹ̀, ó gé Ráhábù sí wẹ́ẹ́wẹ́.

13. Nípa ẹ̀mí rẹ̀ ni ó ti ṣe ọ̀run níọ̀sọ́; ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti dá ejò wíwo nì.

14. Kíyèsí i, èyí ní òpin ọ̀nà rẹ̀;ohùn èyí tí a gbọ́ ti kéré tó!Ta ni ẹni náà tí òye àrá agbára rẹ̀ lè yé?”

Ka pipe ipin Jóòbù 26