Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 24:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Se bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmárè fún ìdájọ́, èéṣe tíojúlùmọ̀ rẹ̀ kò fi rí ọjọ́ rẹ̀?

2. Díẹ̀ nínú wọn a ṣún àmì ààlà ilẹ̀,wọ́n á fi agbára kó agbo ẹran lọ, wọ́n sì ji wọn.

3. Wọ́n á sì dà kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní babalọ, wọ́n a sì gba ọ̀dá-màlúù opó ní ohun ògo.

4. Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà,àwọn talákà àyé a sá pamọ́ pọ̀.

5. Kíyèsí i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́ nínú ijùni àwọn talákà ijáde lọ sí iṣẹ́wọn; Wọ́n a tètè dìde láti wáohun ọdẹ; ijù pèsè oúnjẹ fúnwọn àti fún àwọn ọmọ wọn

6. Olúkulùkù a sì ṣa ọkà oúnjẹ ẹranrẹ̀ nínú oko, wọn a sì ká ọgbà àjàrà ènìyàn búburú.

7. Ní hòòhò ni wọn má a sùn láìní aṣọ,tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.

8. Ọ̀wàrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,wọ́n sì lẹ̀mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.

9. Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò níẹnu ọmú, wọ́n sì gbà ọmọ talákà. Nítorí gbèsè

10. Wọ́n rìn kiri níhòòhò láìní aṣọ;àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà,

11. Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínúàgbàlá wọn, tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntíàjàrà, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.

12. Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́kígbe sókè; fún ìrànlọ́wọ́ ṣíbẹ̀Ọlọ́run kò kíyèsí àṣìṣe náà.

13. “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó kọ̀ìmọ́lẹ̀; Wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.

Ka pipe ipin Jóòbù 24