Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 22:15-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ìwọ fẹ́ rìn ìpa ọ̀nà ìgbàanì tí àwọnènìyàn búburú tí rìn?

16. A ké wọn lulẹ̀ kúrò nínú ayéláìpé ọjọ́ wọn; ìpilẹ̀ wọn ti dé bí odò síṣàn;

17. Àwọn ẹni tí ó wí fún Ọlọ́run pé,lọ kúrò lọ́dọ̀ wa! Kí niOlódùmárè yóò ṣe fún wọn?

18. Ṣíbẹ̀ ó fi ohun rere kún ilé wọn!Ṣùgbọ́n ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi!

19. “Àwọn olódodo rí ìparun wọn,wọ́n sì yọ̀, àwọn aláìlẹ̀ṣẹ̀ sì fi wọ́n rẹ́rìn ín ẹlẹ́yà pé,

20. Lótìítọ́ àwọn ọ̀ta wa ni a ké kúrò, ináyóò sì jó oró wọn run.

21. “Fa ara rẹ súnmọ́ Ọlọ́run, ìwọ ó sìrí àlàáfíà; Pẹ̀lú rẹ̀ nípa èyí ni rere yóò wá bá ọ.

22. Èmi bẹ̀ ọ́, gba òfin láti ẹnu rẹ̀wá, kí o sì tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ sí àyà rẹ.

23. Bí ìwọ bá yípadà sọ́dọ̀Olódùmáarè, a sì gbé ọ ró, bíìwọ bá sì mú ẹ̀ṣẹ̀ jìnnà réré kúrò nínú àgọ́ rẹ,

24. Tí ìwọ bá tẹ́ wúrà dáradára sílẹ̀lórí erùpẹ̀ àti wúrà ófiri lábẹ́ òkúta odò,

25. Nígbà náà ní Olódùmáarè yóò jẹ́wúrà rẹ, àní yóò sì jẹ́ fàdákà fún ọ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.

26. Lótìítọ́ nígbà náà ní ìwọ ó ní inúdídùn nínú Olódùmáarè, ìwọ ósì gbé ojú rẹ sókè sọ́dọ̀ Ọlọ́run.

27. Bí ìwọ bá gbàdúrà rẹ sọ́dọ̀ rẹ̀,yóò sì gbọ́ tìrẹ, ìwọ ó sì san ẹ̀jẹ́ rẹ.

28. Ìwọ ó sì gbìmọ̀ ohun kan pẹ̀lú,yóò sì fi ìdí múlẹ̀ fún ọ; ìmọ́lẹ̀ yóò sì mọ́ sípa ọ̀nà rẹ.

29. Nígbà tí ipa-ọ̀nà rẹ bá lọ sísàlẹ̀,nígbà náà ni ìwọ o wí pé, ‘Ìgbésókè ń bẹ!’Ọlọ́run yóò sì gba onírẹ̀lẹ̀ là!

Ka pipe ipin Jóòbù 22