Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 21:27-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Kíyèsí i, èmi mọ̀ ìrò inú yín àtiàrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.

28. Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní iléọmọ aládé, àti níbo ní àgọ́àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’

29. Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjálọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn, pé

30. Ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fúnọjọ́ ìparun? A ó sì mú wọnjáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.

31. Ta ni yóò sọ ipa ọ̀nà rẹ̀ kò ó níojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?

32. Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ósì máa ṣọ́ ibojì òkú.

33. Ògúlùtù àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn.Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ ṣíwájú rẹ̀.

34. “Èé ha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínúlásán, bí ò ṣepé ní ìdáhùn yín, eké kù níbẹ̀!”

Ka pipe ipin Jóòbù 21