Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 21:13-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Wọ́n ní ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọnsì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà.

14. Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fúnỌlọ́run pé, lọ kúrò lọ́dọ̀ wa,nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ!

15. Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máasìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?

16. Kíyè sí i, àlàáfíà wọn kò sí nípaọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí ni réré.

17. “Ìgbà mélòómélòó ní a ń pa iná ènìyànbúburú kú? Ìgbà mélòómélòó ní ìparunwọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì ímáa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?

18. Wọ́n dàbí àkékù oko níwájúafẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹfúùfù ńlá fẹ́ lọ.

19. Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to iya ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.

20. Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóòsì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.

21. Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilérẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?

22. “Ẹnikẹ́ni le íkọ́ Ọlọ́run ní ìmọ̀?Òun ní í sáa ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.

23. Ẹnìkan a kú nínu pípé agbára rẹ̀,ó wà nínú ìrọra àti ìdákẹ́ pátapáta.

24. Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú,egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.

25. Ẹlòmìíràn a sì kú ninú kíkoròọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.

26. Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínúerùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.

27. “Kíyèsí i, èmi mọ̀ ìrò inú yín àtiàrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.

28. Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní iléọmọ aládé, àti níbo ní àgọ́àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’

Ka pipe ipin Jóòbù 21