Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 21:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jóòbù wá dahùn, ó sì wí pé:

2. “Ẹ tẹ́tí silẹ̀ dẹdẹ sì àwọn ọ̀rẹ́ mi,kí èyí kí ó jásí ìtùnú tí ó fún mi.

3. Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbàtí mo bá sọ tán, ìwọ máa fi ṣẹ̀sín ń ṣo.

4. “Bí ó ṣe tí èmi ni, àròyé mi iṣe sí ènìyàn bí?Tàbí èétíṣe tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?

5. Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín,kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.

6. Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí,ìwárìrì sì mú mi lára.

7. Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà níayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?

8. Irú ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojúwọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ-ọmọ wọn ní ojú wọn.

9. Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ni ọ̀pá iná Ọlọ́run kò sí lára wọn.

10. Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì ísìíṣe; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun;

11. Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọnwẹ́ẹ́wẹ́ẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jó kiri.

12. Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àtiháápù, wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè

13. Wọ́n ní ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọnsì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà.

14. Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fúnỌlọ́run pé, lọ kúrò lọ́dọ̀ wa,nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ!

Ka pipe ipin Jóòbù 21