Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 12:17-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòòhò,A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18. Ó tú ìdè ọba,Ó sì fi mú àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

19. Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòòhò,Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.

20. Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,Ó sì ra àwọn àgbààgbà ní iyè.

21. Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́là,Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.

22. Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.

23. Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.

24. Òun a gba àyà olú àwọn ènìyàn aráyé,A sì máa mú wọn wọ́ kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.

25. Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,Òun a sì máa mú wọn tàsé ìrìn bí ọ̀mùtí.

Ka pipe ipin Jóòbù 12