Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 11:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,

14. Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.

15. Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láì ní àbàwọ́n,àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,

16. Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti ṣàn kọjá lọ.

17. Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísisinyìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.

Ka pipe ipin Jóòbù 11