13. “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
14. Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.
15. Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láì ní àbàwọ́n,àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,
16. Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti ṣàn kọjá lọ.
17. Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísisinyìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.