Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 9:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Áà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijéÈmi yóò sì sunkún tọ̀sán tòrunítorí pípa àwọn ènìyàn mi.

2. Áà! èmi ìbá ní ilé àgbàwọ̀ fúnàwọn arìnrìn-àjò ní ihà kí nba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn:nítorí gbogbo wọn jẹ́ pańṣágààjọ aláìsòótọ́ ènìyàn ni wọ́n.

3. Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfàláti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òótọ́ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ńlọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn,wọn kò sì náání mi,ní Olúwa wí.

4. Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣegbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹnítorí pé oníkálukú arákùnrinjẹ́ atannijẹ, oníkálukú ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.

5. Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì sí ẹnitó sọ òótọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọnláti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọndi onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀

6. Ó ń gbé ní àárin ẹ̀tànwọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínúẹ̀tàn wọn,ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 9