Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 51:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ohùn ti Olúwa nìyìí:“wò ó èmi yóò ru ẹ̀míapanirun kan sókè síBábílónì àwọn ènìyàn Lébíkámáì

2. Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn síBábílónì láti ba ilẹ̀ jẹ́,wọn yóò ṣe àtakò rẹ̀ ní gbogboọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.

3. Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀jáde tàbí kí o di ìhámọ́ra rẹ̀;má ṣe dá àwọn ọdọ́mọkùnrinsí, pátapáta ni kí o pa àwọn ọmọ ogun rẹ̀.

4. Gbogbo wọn ni yóò ṣubúní Bábílónì tí wọn yóò sìfarapa yánna yànna ní òpópónà.

5. Nítorí pé Júdà àti Ísírẹ́lì niỌlọ́run wọn tí í se Olúwa alágbárakò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọnkún fún kìki ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì.

6. “Sá kúrò ní Bábílónì! Sá àsálàfún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.Àsìkò àti gbẹ̀san Ọlọ́run ni èyí,yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.

7. Ifẹ́ wúrà ni Bábílónì ní ọwọ́ Olúwa;ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí.Gbogbo orílẹ̀ èdè mu ọtí rẹ̀,wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.

8. Bábílónì yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́;sunkún fún un! Wá báàmù fún ìrora rẹ,bóyá yóò le wo ọ́ sàn.

9. “ ‘À bá ti wo Bábílónì sàn,ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀,kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè,ó ga àní títí dé òfurufù.’

10. “ ‘Olúwa ti dá wa láre,wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Síónì ohun tí OlúwaỌlọ́run wa ti ṣe.’

11. “Lọ ọfà wa kó mú, mú apata! Olúwa ti ru Ọba Médíà sókè,nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Bábílónì run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún Tẹ́ḿpìlì rẹ̀.

Ka pipe ipin Jeremáyà 51