Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 50:25-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Olúwa ti kó àwọn ohun èlòìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé OlúwaỌlọ́run ọmọ ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Bábílónì.

26. Ẹ dìde sí láti ilẹ̀ jínjínpárun pátapáta láìṣẹ́kù.

27. Pa gbogbo àwọn ọ̀dọ́àgùntàn rẹ̀, jẹ́ kí a kówọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n!Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé,àkókò ìbẹ̀wò wọn.

28. Tẹ́tí sí àwọn tí ó sálọ tí ó sì sálà láti Bábílónì,sì sọ ní Síónì, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san,ẹ̀san fún tẹ́ḿpílì rẹ̀.

29. “Pe ọ̀pọ̀lopọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Bábílónì,ẹ doti iyikakiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà.Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbógbó èyí ti o ti ṣé,ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ síi, nítorí tí ó ti gberagasí Olúwa, sí Ẹni-MÍMỌ̀ Ísirẹ́lì.

30. Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọnológun lẹ́nu mọ́,”ní Olúwa wí.

31. “Wò ó, èmi lòdì sí àwọn onígbéraga,”ni Olúwa Ọlọ́run,“ọmọ ogun wí, nítorí ọjọ́ rẹti dé tí ìwọ yóò jìyà.

32. Onígbéraga yóò kọsẹ̀, yóòsì ṣubú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò gbé dìde.Èmi yóò tan iná ní ìlú náà,èyí tí yóò sì jo run.”

33. Èyí ni ohun tí Olúwa alágbára sọ:“A pọ́n àwọn ènìyàn Ísírẹ́lìlójú àti àwọn ènìyàn Júdà pẹ̀lú.Gbogbo àwọn tí ó kó wọnnígbèkùn dì í mú ṣinṣinwọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálá.

34. Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run alágbára ni orúkọ rẹ̀.Yóò sì gbe ìjà wa jà,kí ó ba à lè mú wọn wá sinmí ní ilẹ̀ náà;àmọ́ kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Bábílónì.

35. “Idà lórí àwọn Bábílónì!”ni Olúwa wí,“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Bábílónì,àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.

36. Idà lórí àwọn wòlíì èkéwọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.

Ka pipe ipin Jeremáyà 50